阿摩司书 3 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

阿摩司书 3:1-15

责备以色列人

1以色列人啊,

要听耶和华责备你们的话,

责备我从埃及领出来的整个民族的话,

2‘世上万族之中,我只拣选了你们,

所以我要因你们的罪恶而惩罚你们。’”

3若非相约,

二人怎会同行呢?

4若非捕到猎物,

狮子怎会在林中咆哮呢?

若非猎获食物,

猛狮怎会在洞中吼叫呢?

5若非设下诱饵,

鸟儿怎会陷入网罗呢?

若非有什么陷进去,

网罗怎会收起来呢?

6若城中响起号角,

居民岂不恐惧颤抖?

若灾祸降临城中,

岂不是耶和华的作为?

7的确,主耶和华不向祂的仆人——众先知显明祂的计划,

就不会采取任何行动。

8狮子吼叫,谁不惧怕呢?

主耶和华已发言,谁能不传讲呢?

9要向亚实突埃及的城堡宣告:

“你们要聚集到撒玛利亚的山上,

看看城中的混乱和暴虐之事。

10他们不知正道,强取豪夺,

在他们的堡垒中积敛钱财。

这是耶和华说的。”

11所以,主耶和华说:

“敌人要围攻此地,

攻破他们的防守,

抢掠他们的城堡。”

12耶和华说:

“牧人从狮口中救羊,

只能夺回两条腿和一块耳朵。

同样,住在撒玛利亚以色列人被救回的时候,

也仅剩一片床榻和一角卧椅。”

13主——万军之上帝耶和华说:

“你们要听这话,去警告雅各家。

14我追讨以色列人的罪时,

要摧毁伯特利的祭坛,

将祭坛的角砍落在地。

15我要拆毁过冬和避暑的房屋,

捣毁象牙装饰的宫殿,

推倒许多宏伟的楼宇。

这是耶和华说的。”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 3:1-15

Ẹ̀rí jíjẹ́ nípa àwọn ọmọ Israẹli

1Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:

2“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn

nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí;

nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà

fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”

3Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀

láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?

4Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó,

bí kò bá ní ohun ọdẹ?

Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀

bí kò bá rí ohun kan mú?

5Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀

nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un?

Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀

nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?

6Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú,

àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù?

Tí ewu bá wa lórí ìlú

kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?

73.7: If 10.7.Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan

láìfi èrò rẹ̀ hàn

fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.

8Kìnnìún ti bú ramúramù

ta ni kì yóò bẹ̀rù?

Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀

ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?

9Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu

àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti.

“Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria;

Kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀

àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”

10“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí,

“àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”

11Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run;

yóò wó ibi gíga yín palẹ̀

a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”

12Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Bí olusọ-àgùntan ti ń gbà itan méjì

kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan

bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli,

tí ń gbé Samaria kúrò

ní igun ibùsùn wọn

ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”

13“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.

14“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,

Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run;

ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò

yóò sì wó lulẹ̀.

15Èmi yóò wó ilé òtútù

lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru;

ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé

a ó sì pa ilé ńlá náà run,”

ni Olúwa wí.