诗篇 49 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 49:1-20

第 49 篇

财富的虚幻

可拉后裔的诗,交给乐长。

1万民啊,你们要听!

世人啊,

2不论贵贱贫富,都要留心听!

3因为我口出智慧,心思明智。

4我要侧耳听箴言,

弹琴解释人生之谜。

5危难来临,四面被奸诈之徒包围时,我何必惧怕?

6他们倚靠金钱、夸耀财富,

7却不能救赎自己的生命,

也无法向上帝付生命的赎价。

8因为生命的赎价高昂,

无人付得起,

9以致可以永远活着,不进坟墓。

10众所周知,即使智者也要死去,

愚人和庸者也要灭亡,

将他们的财富留给别人。

11尽管他们用自己的名字来为产业命名,

坟墓却是他们永远的归宿,

世代的住处。

12人不能长享富贵,

终必死去,与兽无异。

13这就是愚昧人及其追随者的下场!(细拉)

14他们注定要死,与羊无异,

死亡是他们的牧者;

到了早晨,

他们必被正直人管辖。

他们的躯体必朽烂在坟墓里,

远离自己的豪宅。

15但上帝必救赎我的生命脱离死亡的权势,

接我到祂身边。(细拉)

16因此,见他人财富增多,

日益奢华,

不要害怕。

17因为他们死后什么也带不走,

再不能拥有荣华富贵。

18他们活着时自以为有福,

人们都赞扬他们的成就,

19到头来他们还是要归到祖先那里,

再也看不见光明。

20人有财富,却无明智的心,

无异于必死的兽类。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 49:1-20

Saamu 49

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.

1Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn!

Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.

2Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré

tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!

3Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,

èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá

4Èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe,

èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.

5Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé?

Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,

6Àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn,

tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.

7Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀

padà tàbí san owó ìràpadà fún

Ọlọ́run.

8Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye

kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,

9Ní ti kí ó máa wà títí ayé

láìrí isà òkú.

10Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú,

bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé

wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.

11Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé,

ibùgbé wọn láti ìrandíran,

wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.

12Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́

ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.

13Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó

gbàgbọ́ nínú ara wọn,

àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn,

tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. Sela.

14Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú

ikú yóò jẹun lórí wọn;

ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò,

jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀;

Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́,

isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn.

15Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà

kúrò nínú isà òkú,

yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀.

16Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀.

Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.

17Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú,

ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú

18Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀.

Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.

19Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀

àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.

20Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.