诗篇 41 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 41:1-13

第 41 篇

病中的祷告

大卫的诗,交给乐长。

1善待穷人的有福了!

耶和华必救他们脱离困境。

2耶和华必保护他们,

救他们的性命,

使他们在地上享福,

不让仇敌恶谋得逞。

3他们生病在床,

耶和华必看顾,

使他们康复。

4我祷告说:“耶和华啊,

求你怜悯我,医治我,

因为我得罪了你。”

5我的仇敌恶狠狠地说:

“他何时才会死,

并且被人遗忘呢?”

6他们来看我时,

心怀恶意,满口谎言,

出去后散布流言。

7所有恨我的人都交头接耳,

设计害我。

8他们说:“他患了恶病,

再也起不来了!”

9连我所信赖、吃我饭的挚友也用脚踢我。

10耶和华啊,

求你怜悯我,叫我痊愈,

我好报复他们。

11我知道你喜悦我,

因为你没有让仇敌胜过我。

12你因我正直而扶持我,

让我永远侍立在你面前。

13从亘古到永远,

以色列的上帝耶和华当受称颂。

阿们!阿们!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 41:1-13

Saamu 41

Fún adarí orin. Saamu Dafidi.

1Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní:

Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.

2Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́:

yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀

kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.

3Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀

yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.

4Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi;

wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.

5Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé

“Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”

6Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí,

wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀;

nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.

7Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi;

èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,

8wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin

àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí,

kì yóò dìde mọ́.”

941.9: Jh 13.18.Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé,

ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi,

tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.

10Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi;

gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.

11Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi,

nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.

12Bí ó ṣe tèmi ni

ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi

ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.

13Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli

láé àti láéláé.

Àmín àti Àmín.