诗篇 30 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 30:1-12

第 30 篇

感恩的祷告

大卫的诗,作献殿之歌。

1耶和华啊,我要赞美你,

因为你救我脱离危难,

不让我的仇敌幸灾乐祸。

2我的上帝耶和华啊,

我呼求你,你就医治了我。

3耶和华啊,你从阴间把我救出,

没有让我落入坟墓。

4耶和华忠心的子民啊,

你们要歌颂祂,

赞美祂的圣名。

5因为祂的怒气瞬间消逝,

祂的恩惠却持续一生。

我们虽然整夜哭泣,

早晨必定欢呼。

6我在顺境中曾说:

“我永不动摇。”

7耶和华啊,

你向我施恩,我便稳固如山;

你掩面不理我,我就惊慌失措。

8耶和华啊,我向你呼求,

恳求你怜悯,说:

9“耶和华啊,

我被毁灭、落入坟墓有何益处?

我归于尘土,还能赞美你、

宣扬你的信实吗?

10耶和华啊,求你垂听我的呼求,怜悯我!

耶和华啊,求你帮助我!”

11你把我的哀哭变成了舞步,

为我脱下悲伤的麻衣,

披上喜乐的外袍,

12好叫我从心底歌颂你,

不致默然无声。

我的上帝耶和华啊,

我要永远向你感恩!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 30:1-12

Saamu 30

Saamu. Orin. Fún ìyàsímímọ́ Tẹmpili. Ti Dafidi.

1Èmi yóò kókìkí i rẹ, Olúwa,

nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékè

tí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ mí.

2Olúwa Ọlọ́run mi, èmi ké pè ọ́, fún ìrànlọ́wọ́

ìwọ sì ti wò mí sàn.

3Olúwa, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkú,

mú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má ba à lọ sínú ihò.

4Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ẹ̀yin olódodo;

kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ̀ mímọ́.

5Nítorí pé ìbínú rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀,

ojúrere rẹ̀ wà títí ayérayé;

Ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́,

Ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀.

6Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé,

“a kì yóò ṣí mi ní ipò padà.”

7Nípa ojúrere rẹ, Olúwa,

ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára;

ìwọ pa ojú rẹ mọ́,

àyà sì fò mí.

8Sí ọ Olúwa, ni mo ké pè é;

àti sí Olúwa ni mo sọkún fún àánú:

9“Èrè kí ni ó wà nínú ikú ìparun mi,

nínú lílọ sí ihò mi?

Eruku yóò a yìn ọ́ bí?

Ǹjẹ́ yóò sọ nípa òdodo rẹ?

10Gbọ́, Olúwa, kí o sì ṣàánú fún mi;

ìwọ Olúwa, jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi.”

11Ìwọ ti yí ìkáàánú mi di ijó fún mi;

ìwọ sì ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mi, o sì fi aṣọ ayọ̀ wọ̀ mí,

12nítorí ìdí èyí ni kí ọkàn mi máa yìn ọ́, kí o má sì ṣe dákẹ́.

Ìwọ Olúwa Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ títí láé.