诗篇 17 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 17:1-15

第 17 篇

无辜者的祈祷

大卫的祈祷。

1耶和华啊,

求你听我祈求公义的声音,

侧耳听我的呼求,

垂听我真诚的祷告。

2愿你宣判我无罪,

愿你明察是非。

3你试验过我的心思,

夜间鉴察过我,磨炼过我,

找不出任何过犯;

我立志口不犯罪。

4我遵守你的教导,洁身自守,

不与残暴之徒同流。

5我坚定地走你的道路,

从未偏离。

6上帝啊!我向你祈祷,

因为你必应允我。

求你垂听我的祷告。

7求你彰显你奇妙的慈爱,

用右手拯救投靠你的人脱离仇敌。

8求你保护我,像保护眼中的瞳仁,

用你的翅膀荫庇我,

9救我脱离恶人的攻击,

脱离四围杀气腾腾的仇敌。

10他们良心丧尽,口出狂言。

11他们穷追围堵,

伺机把我打倒在地。

12他们像急于撕碎猎物的饿狮,

又像蹲伏在暗处的猛狮。

13耶和华啊,

求你起来迎头击倒他们,

求你持刀救我脱离恶人。

14耶和华啊,

求你伸手救我脱离这些人,

脱离这些只在今生有福分的世人。

你使他们财宝无数。

他们儿女众多,

还把财富留给子孙。

15但我因持守公义必见你的面;

我醒来见到你就心满意足了。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 17:1-15

Saamu 17

Àdúrà ti Dafidi

1Gbọ́, Olúwa, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi;

fi etí sí igbe mi.

Tẹ́tí sí àdúrà mi

tí kò ti ètè ẹ̀tàn jáde.

2Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ;

kí ojú rẹ kí ó rí ohun tí ó tọ́.

3Ìwọ ti dán àyà mi wò,

ìwọ sì bẹ̀ mí wò ní òru, o sì ti wádìí mi,

ìwọ kì yóò rí ohunkóhun èmi ti pinnu pé,

ẹnu mi kì yóò ṣẹ̀.

4Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ,

èmi ti pa ara mi mọ́

kúrò ní ọ̀nà àwọn ìkà.

5Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ;

ẹsẹ̀ mi kì yóò yọ̀.

6Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn

dẹ etí rẹ sí mi kí o sì gbọ́ àdúrà mi.

7Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn

ìwọ tí ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là

lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.

8Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ;

fi mí pamọ́ sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ,

9lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi,

kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.

10Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́,

wọ́n sì fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga.

11Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká,

pẹ̀lú ojú ìṣọ́ra láti ṣọ́ mi sílẹ̀.

12Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ,

àní bí kìnnìún ńlá tí ó ń ba níbi ìkọ̀kọ̀.

13Dìde, Olúwa, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀;

gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹni búburú nípa idà rẹ.

14Olúwa, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀,

kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn ayé yìí, tí èrè wọn wà nínú ayé yìí.

Ìwọ ń pa ebi àwọn tí ìwọ fẹ́ràn lẹ́nu mọ́;

àwọn ọmọ wọn sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀,

wọ́n sì kó ọrọ̀ jọ fún àwọn ọmọ wọn.

15Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo;

nígbà tí èmi bá jí, èmi yóò ní ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí èmi bá rí àwòrán rẹ.