约伯记 33 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

约伯记 33:1-33

1约伯啊,请听我言,

请留心听我每一句话。

2我要开口发言,

我话已在舌尖。

3我的话发自正直的心,

我的口如实陈明道理。

4上帝的灵创造了我,

全能者的气赋予我生命。

5如果你能,就反驳我,

站出来与我辩论。

6在上帝面前,我与你无异,

也是泥土造的。

7所以你不用惧怕我,

我不会对你施加压力。

8“你的话已进到我耳中,

我听见你说,

9‘我纯全无过,

我清白无罪,

10上帝却挑我的错,

与我为敌;

11祂给我戴上脚镣,

鉴察我的一举一动。’

12“我来答复你,你的话没有道理,

因为上帝比世人大。

13你为何向祂抱怨,

说祂不理会世人的话?

14上帝一再用各种方式说话,

然而世人却不明白。

15人躺在床上沉睡时,

在梦境和夜间的异象中,

16上帝开启他们的耳朵,

用警告惊吓他们,

17使他们离开罪恶,

不再骄傲,

18以免他们的灵魂坠入深坑,

他们的性命被刀剑夺去。

19“人因受罚而卧病在床,

骨头疼痛不止,

20以致毫无食欲,

对佳肴心生厌恶。

21他日渐消瘦,

只剩下骨头。

22他的灵魂临近深坑,

他的生命濒临死亡。

23如果一千天使中有一位能做他的中保,

指示他当行的事,

24上帝33:24 上帝”希伯来文是“他”,也可能指天使。就会怜悯他,说,‘别让他下坟墓,

我已得到他的赎金。’

25那时,他的皮肉将嫩如孩童,

他将恢复青春的活力。

26他向上帝祷告时必蒙悦纳,

他欢呼着朝见上帝,

再度被祂视为义人。

27他会当众歌唱说,

‘我犯了罪,颠倒是非,

祂却没有按我的罪报应我。

28祂救赎我的灵魂,使之免下深坑,

使我的生命得见光明。’

29“看啊,这都是上帝的作为,

祂一次次地恩待世人,

30从深坑救回人的灵魂,

使他沐浴生命之光。

31约伯啊,留心听我说,

不要作声,我要发言。

32你若有话,就答复我;

你只管说,我愿看到你的清白。

33否则,请听我言;

不要作声,我要传授你智慧。”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 33:1-33

Elihu bá Jobu sọ̀rọ̀

1“Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ,

gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!

2Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi,

ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.

3Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi,

ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.

4Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi,

àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.

5Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn,

tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;

6Kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà;

láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.

7Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ;

bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.

8“Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi,

èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,

9‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi;

bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.

10Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi;

ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.

11Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà;

o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’

12“Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà!

Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!

13Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé,

òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?

14Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan,

àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.

15Nínú àlá, ní ojúran òru,

nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ,

ní sísùn lórí ibùsùn,

16Nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn,

yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,

17Kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀;

Kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;

18Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú,

àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.

19“A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀;

pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,

20bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ,

ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.

21Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́

egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.

22Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú,

ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.

23Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀,

ẹni tí ń ṣe alágbàwí,

ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,

24Nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé,

gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú;

èmi ti rà á padà.

25Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré,

yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;

26Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀,

o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀,

òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.

27Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé,

‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po,

a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;

28Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò,

ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’

29“Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run

máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,

30Láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú,

láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.

31“Jobu, kíyèsi i gidigidi kí o sì fetí sí mi;

pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́

32Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn;

máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.

33Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi;

pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”