约伯记 16 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

约伯记 16:1-22

约伯的回答

1约伯回答说:

2“这些话,我听过很多,

你们安慰人,反让人愁烦。

3你们的空谈无休无止吗?

是什么惹你们说个不停?

4倘若你我易地而处,

我也能说你们那样的话,

滔滔不绝地攻击你们,

向你们摇头。

5我会对你们讲鼓励的话,

用劝慰之言减轻你们的痛苦。

6“我若申辩,痛苦不减;

我若缄默,痛苦犹在。

7上帝啊,你使我精疲力竭,

家破人亡,

8你榨干了我,

使我骨瘦如柴,

这成了我的罪证。

9上帝在愤怒中撕裂我,迫害我,

向我咬牙切齿;

仇敌恶狠狠地盯着我。

10他们嘲笑我,

轻蔑地掴我的脸,

联合起来攻击我。

11上帝把我交给罪人,

把我扔到恶人手中。

12我本来平顺,祂击垮了我,

祂抓住我的颈项将我摔碎,

把我当祂的箭靶。

13祂的弓箭手四面围住我,

祂毫不留情地刺透我的肾脏,

使我肝胆涂地。

14祂一次次地击伤我,

像勇士一样扑向我。

15我缝制麻衣,披在身上,

把我的荣耀埋在尘土中。

16我哭得脸颊红肿,

眼皮发黑。

17但我未行残暴之事,

我的祷告纯真。

18“大地啊!不要掩盖我的血,

不要拦阻我的呼求。

19此时,我的见证人在天上,

我的辩护者在高天上。

20我的朋友讥笑我,

我在上帝面前流泪。

21但愿人与上帝之间有仲裁者,

如同人与人之间。

22因为我的年日不多,

我快要踏上不归路。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 16:1-22

Ìdáhùn Jobu fún Elifasi

1Ìgbà náà ní Jobu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Èmi ti gbọ́ irú ohun púpọ̀ bẹ́ẹ̀ rí

ayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.

3Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin?

Tàbí kí ni ó gbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?

4Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin;

bí ọkàn yín bá wà ní ipò ọkàn mi,

èmi le sọ ọ̀rọ̀ dáradára púpọ̀ sí yín ní ọrùn,

èmi a sì mi orí mi sí i yín.

5Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín ni

ìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.

6“Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò lọ;

bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí ko kúrò?

7Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá mi lágara;

Ìwọ Ọlọ́run mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.

8Ìwọ fi ìhunjọ kùn mí lára, èyí tí o jẹ́rìí tì mí;

àti rírù tí ó hàn lára mi, ó jẹ́rìí tì mí ní ojú.

9Ọlọ́run fi i ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ó sì gbóguntì mí;

ó pa eyín rẹ̀ keke sí mi,

ọ̀tá mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.

10Wọ́n ti fi ẹnu wọn yẹ̀yẹ́ mi;

Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbá ẹ̀gàn;

Wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.

11Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹni

búburú, ó sì mú mi ṣubú sí ọwọ́ ènìyàn ìkà.

12Mo ti jókòó jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n ó fà mí já;

ó sì dì mí ni ọrùn mú, ó sì gbọ̀n mí túútúú,

ó sì gbé mi kalẹ̀ láti ṣe ààmì ìtafàsí rẹ̀;

13àwọn tafàtafà rẹ̀ dúró yí mi káàkiri.

Ó là mí láyà pẹ̀rẹ̀, kò si dá sí,

ó sì tú òróòro ara mi dà sílẹ̀.

14Ìbàjẹ́ lórí ìbàjẹ́ ní ó fi bà mí jẹ́;

ó súré kọlù mi bí jagunjagun.

15“Mo rán aṣọ ọ̀fọ̀ bò ara mi,

mo sì rẹ̀ ìwo mi sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.

16Ojú mi ti pọ́n fún ẹkún,

òjìji ikú sì ṣẹ́ sí ìpéǹpéjú mi.

17Kì í ṣe nítorí àìṣòótọ́ kan ní ọwọ́

mi; àdúrà mi sì mọ́ pẹ̀lú.

18“Háà! Ilẹ̀ ayé, ìwọ má ṣe bò ẹ̀jẹ̀ mi,

kí ẹkún mi má ṣe wà ní ipò kan.

19Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi i, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ ní ọ̀run,

ẹ̀rí mi sì ń bẹ lókè ọ̀run.

20Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣẹ̀sín,

ṣùgbọ́n ojú mi ń da omijé sọ́dọ̀ Ọlọ́run;

21Ìbá ṣe pé ẹnìkan le è máa ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọ́run,

bí ènìyàn kan ti í ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì rẹ̀.

22“Nítorí nígbà tí iye ọdún díẹ̀ rékọjá tán,

nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà bọ̀.