约书亚记 14 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

约书亚记 14:1-15

约旦河西土地的分配

1以下是祭司以利亚撒的儿子约书亚以色列各支派的首领在迦南分给以色列人的产业, 2是照耶和华给摩西的指示,用抽签的方式分给九个半支派的。 3摩西约旦河东已经把产业分给了吕便迦得支派和玛拿西半个支派,只是没有把产业分给利未人。 4约瑟的子孙已分为玛拿西以法莲两个支派。利未人没有分到地,但有城邑居住,还有城郊可以牧养牲畜,安置财物。 5以色列人照耶和华给摩西的指示分配这些土地。

迦勒分得希伯仑

6那时,犹大支派的人来到吉甲约书亚,其中有基尼洗耶孚尼的儿子迦勒。他对约书亚说:“你知道耶和华在加低斯·巴尼亚跟上帝的仆人摩西提到关于你和我的事。 7我四十岁那年,耶和华的仆人摩西加低斯·巴尼亚派我来侦察这地方,我如实禀告他。 8与我同去的弟兄的禀告令以色列人胆战心惊,但我忠心地追随我的上帝耶和华。 9所以,当日摩西就向我起誓,‘你脚踏过的地方必永远归你和你的子孙作产业,因为你忠心地追随我的上帝耶和华。’ 10耶和华照祂的应许,让我又活了四十五年,这些日子都是跟以色列人在旷野一起度过的。看!我现在已经八十五岁了, 11仍像当年摩西派我出去时那样身强力壮,跟当年一样能征善战。 12现在,求你照耶和华当日向我应许的,把这山区赐给我。你亲耳听到那里有亚衲人,他们的城池高大坚固。但如果耶和华与我同在,我必照着祂的应许把这些人赶走。”

13于是,约书亚便祝福耶孚尼的儿子迦勒,把希伯仑给他,作为他的产业。 14所以,希伯仑至今仍是基尼洗耶孚尼的儿子迦勒的产业,因为他忠心地追随以色列的上帝耶和华。 15希伯仑从前名叫基列·亚巴,亚巴原是亚衲族中最伟大的人。从此,境内太平,没有战争。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joṣua 14:1-15

Pínpín ilẹ̀ ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani

1Ìwọ̀nyí ni ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà gẹ́gẹ́ bí ogún ní ilẹ̀ Kenaani, tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn agbo ilé Israẹli pín fún wọn. 2Ìbò ni a fi pín ìní wọn fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án ààbọ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ọwọ́ Mose. 3Mose ti fún àwọn ẹ̀yà méjì àti ààbọ̀ ní ogún wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi ni kò fi ìní fún ní àárín àwọn tí ó kù. 4Àwọn ọmọ Josẹfu sì di ẹ̀yà méjì, Manase àti Efraimu. Àwọn ọmọ Lefi kò gba ìpín ní ilẹ̀ náà bí kò ṣe àwọn ìlú tí wọn yóò máa gbé, pẹ̀lú pápá oko tútù fún ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran wọn. 5Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli pín ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

A fún Kalebu ní Hebroni

6Àwọn ọkùnrin Juda wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní Gilgali. Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti wí fún un pé, “Ìwọ rántí ohun tí Olúwa sọ fún Mose ènìyàn Ọlọ́run ní Kadeṣi-Barnea nípa ìwọ àti èmi. 7Mo jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa rán mi láti Kadeṣi-Barnea lọ rin ilẹ̀ náà wò. Mo sì mú ìròyìn wá fún un gẹ́gẹ́ bí o ti dá mi lójú, 8ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin mi tí wọ́n bá mi lọ mú àyà àwọn ènìyàn já. Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi fi gbogbo ọkàn tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run mi. 9Ní ọjọ́ náà, Mose búra fún mi pé, ‘Ilẹ̀ tí ẹsẹ̀ rẹ ti rìn ni yóò jẹ́ ìní rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ láéláé, nítorí pé ìwọ fi tọkàntọkàn wà pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run mi.’

10“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kíyèsi i Olúwa dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ó ti wí, láti ọdún márùn-ún-dínláàádọ́ta yìí wá, láti ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Mose, nígbà tí Israẹli ń rìn kiri nínú aginjù, sì kíyèsi i nísinsin yìí, èmi nìyìí lónìí, ọmọ àrùndínláàdọ́rùnún ọdún. 11Síbẹ̀ èmi ní agbára lónìí, bí ìgbà tí Mose rán mi jáde. Èmi sì ní agbára láti jáde fún ogun nísinsin yìí gẹ́gẹ́ bí mo ti wà ní ìgbà náà. 12Nísinsin yìí fi ìlú orí òkè fún mi èyí tí Olúwa ṣe ìlérí fún mi ní ọjọ́ náà. Ìwọ gbọ́ ní ìgbà náà pé àwọn ọmọ Anaki ti wà ní ibẹ̀, àti àwọn ìlú wọn tóbi, pé ó sì ṣe olódi, ṣùgbọ́n bí Olúwa ba fẹ́, èmi yóò lé wọn jáde, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ.”

13Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua súre fun Kalebu ọmọ Jefunne ó si fun un ní Hebroni ni ilẹ̀ ìní 14Bẹ́ẹ̀ ni Hebroni jẹ́ ti Kalebu ọmọ Jefunne ará Kenissiti láti ìgbà náà, nítorí tí ó tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tọkàntọkàn. 15(Hebroni a sì máa jẹ́ Kiriati-Arba ní ẹ̀yìn Arba, èyí tí ó jẹ́ ènìyàn ńlá nínú àwọn ọmọ Anaki.)

Nígbà náà ni ilẹ̀ náà sinmi ogun.