撒母耳记上 31 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

撒母耳记上 31:1-13

扫罗之死

1非利士人与以色列人交战,以色列人败逃,许多人在基利波山被杀。 2非利士人穷追扫罗及其众子,杀了扫罗的儿子约拿单亚比拿达麦基舒亚3扫罗周围战事激烈,他被弓箭手发现、射成重伤, 4就对为他拿兵器的人说:“拔出你的刀来刺死我吧,免得那些未受割礼的人来刺杀和凌辱我。”但拿兵器的人非常害怕,不敢动手,扫罗就自己伏刀自尽了。 5侍从看见扫罗已死,也伏刀自尽了。 6这样,扫罗和他三个儿子,以及为他拿兵器的人和他的军队都死了。 7平原一带和约旦河对面的以色列人见以色列军败逃、扫罗及其众子已死,都弃城而逃。于是,非利士人占据了那些城邑。

8次日,非利士人来剥阵亡者的衣物,发现扫罗和他的三个儿子横尸基利波山, 9就割下了扫罗的头颅,剥下他的盔甲,并派人走遍非利士全境,在他们偶像的庙里及民众中通告消息。 10非利士人把扫罗的盔甲放在亚斯她录神庙里,把他的尸体钉在伯·珊城墙上。 11基列·雅比人听说非利士人对扫罗的所作所为, 12他们所有的勇士就连夜赶到伯·珊,从墙上取下扫罗和他儿子们的尸体,带到雅比火化, 13把骨灰葬在雅比的垂丝柳树下,又为他们禁食了七天。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Samuẹli 31:1-13

Saulu pa ara rẹ̀

131.1-13: 2Sa 1.6-10; 1Ki 10.1-12.Nísinsin yìí, àwọn ará Filistini dojú ìjà kọ Israẹli, Àwọn ará Israẹli sì sálọ kúrò níwájú wọn, a sì pa ọ̀pọ̀ wọn sí orí òkè Gilboa 2Àwọn Filistini sì ń lépa Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ kíkan; àwọn Filistini sì pa Jonatani àti Abinadabu, àti Malikiṣua, àwọn ọmọ Saulu. 3Ìjà náà sì burú fún Saulu gidigidi, àwọn tafàtafà si ta á ní ọfà, o sì fi ara pa púpọ̀ lọ́wọ́ àwọn tafàtafà.

4Saulu sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí ìwọ sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má ba à wá gún mi, àti kí wọn kí ó má bá à fi mí ṣe ẹlẹ́yà.”

Ṣùgbọ́n ẹni tí ó rú ẹ̀rù ìhámọ́ra rẹ̀ kò fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí pé ẹ̀rù bà á gidigidi. Nígbà náà ni Saulu mú idà, ó sì ṣubú lù ú. 5Nígbà tí ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ si rí i pé Saulu kú, òun náà sì fi idà rẹ̀ pa ara rẹ̀, ó sì kú pẹ̀lú rẹ̀. 6Saulu sì kú, àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta, àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.

7Nígbà ti àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó wà lápá kejì àfonífojì náà, àti àwọn ẹni tí ó wà lápá kejì Jordani, rí pé àwọn ọkùnrin Israẹli sá, àti pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ ti kú, wọ́n sì fi ìlú sílẹ̀, wọ́n sì sá, àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì jókòó si ìlú wọn.

8Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn Filistini dé láti bọ́ nǹkan tí ń bẹ lára àwọn tí ó kù, wọ́n sì rí pé, Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta ṣubú ni òkè Gilboa. 9Wọ́n sì gé orí rẹ̀, wọ́n sì bọ ìhámọ́ra rẹ̀, wọ́n sì ránṣẹ́ lọ ilẹ̀ Filistini káàkiri, láti máa sọ ọ́ ní gbangba ni ilé òrìṣà wọn, àti láàrín àwọn ènìyàn. 10Wọ́n sì fi ìhámọ́ra rẹ̀ sí ilé Aṣtoreti: wọ́n sì kan òkú rẹ̀ mọ́ odi Beti-Ṣani.

11Nígbà tí àwọn ará Jabesi Gileadi sì gbọ́ èyí tí àwọn Filistini ṣe sí Saulu. 12Gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára sì dìde, wọ́n sì fi gbogbo òru náà rìn, wọ́n sì gbé òkú Saulu, àti òkú àwọn ọmọ bíbí rẹ̀ kúrò lára odi Beti-Ṣani, wọ́n sì wá sí Jabesi, wọ́n sì sun wọ́n níbẹ̀. 13Wọ́n sì kó egungun wọn, wọ́n sì sin wọ́n lábẹ́ igi tamariski ní Jabesi, wọ́n sì gbààwẹ̀ ní ọjọ́ méje.