以赛亚书 50 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

以赛亚书 50:1-11

以色列的罪恶

1耶和华说:

“我休你们母亲的休书在哪里呢?

我把你们卖给了我哪一个债主呢?

你们被卖是因为你们的罪恶,

你们母亲被休是因为你们的过犯。

2为什么我来的时候一个人也不在?

为什么我呼唤的时候没有人回答?

是我的臂膀太短不能救赎你们吗?

是我没有能力拯救你们吗?

看啊,我斥责一声,海就干了;

我使江河变为旷野,

鱼类因无水而干死,发出腥臭。

3我使黑暗遮蔽穹苍,

用麻布掩盖天空。”

主仆的顺服

4主耶和华赐我教导的能力,

使我知道用什么话帮助疲乏的人。

每天早晨,主唤醒我,

叫我像受教者那样侧耳聆听。

5主耶和华开了我的耳朵,

我没有悖逆,也没有退缩。

6人打我的背,我任他打;

人拔我的胡子,我任他拔;

人侮辱我,朝我吐唾沫,

我也不掩面。

7我并不觉得羞愧,

因为主耶和华帮助我。

我心如坚石,

知道自己必不会蒙羞。

8为我伸张正义的来了,

谁要控告我呢?

让我们来理论吧!

谁是我的控告者呢?

让他到我这里来吧!

9看啊,有主耶和华帮助我,

谁能定我有罪呢?

看啊,他们都要像衣服一样渐渐破旧,

被蛀虫吃掉。

信靠上帝

10你们中间谁敬畏耶和华,

听从祂仆人的话?

行在黑暗中、

没有光的人要信靠耶和华的名,

仰赖自己的上帝。

11然而,你们自己生火、自备火把的人啊,

靠自己点燃的火光行走吧!

你们必落入悲惨的境地,

这是耶和华亲手所定的。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 50:1-11

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìgbọ́ràn ìránṣẹ́

1Ohun tí Olúwa wí nìyìí:

“Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà

èyí tí mo fi lé e lọ?

Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi

ni mo tà ọ́ fún?

Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́;

nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.

2Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan?

Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn?

Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́?

Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí?

Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi Òkun,

Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀;

àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi

wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.

3Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀

mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”

4Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán,

láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró.

O jí mi láràárọ̀,

o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.

5Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí;

Èmi kò sì padà sẹ́yìn.

6Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí,

àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi;

Èmi kò fi ojú mi pamọ́

kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.

7Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́;

A kì yóò dójútì mí.

Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ

èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.

8Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí.

Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí?

Jẹ́ kí a kojú ara wa!

Ta ni olùfisùn mi?

Jẹ́ kí ó kò mí lójú!

9Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́.

Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi?

Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ;

kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.

10Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa

tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu?

Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn

tí kò ní ìmọ́lẹ̀,

kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa

kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.

11Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná

tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín,

ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín,

àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá.

Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá:

Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.