Забур 69 – CARST & YCB

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Забур 69:1-6

Песнь 69

(Заб. 39:14-18)

1Дирижёру хора. Песнь Довуда. В напоминание.

2Всевышний, скорее избавь меня!

Поспеши мне на помощь, Вечный!

3Пусть все, кто желает моей смерти,

будут пристыжены и посрамлены.

Пусть все, кто хочет моей погибели,

в бесчестии повернут назад.

4Пусть возвратятся со стыдом

говорящие мне: «Ага! Ага!»

5Пусть ликуют и радуются о Тебе

все ищущие Тебя,

Пусть те, кто любит Тебя за Твоё спасение,

всегда говорят: «Велик Всевышний!»

6Я же беден и нищ.

Поспеши ко мне, Всевышний!

Ты – помощь моя и мой избавитель;

Вечный, не замедли!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 69:1-36

Saamu 69

Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi.

1Gbà mí, Ọlọ́run,

nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.

2Mo ń rì nínú irà jíjìn,

níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé.

Mo ti wá sínú omi jíjìn;

ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.

3Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́;

ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú,

nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.

469.4: Sm 35.19; Jh 15.25.Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí

wọ́n ju irun orí mi; lọ

púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí,

àwọn tí ń wá láti pa mí run

A fi ipá mú mi

láti san ohun tí èmi kò jí.

5Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run;

ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.

6Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ

nítorí mi,

Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun;

Má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi,

Ọlọ́run Israẹli.

7Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn,

ìtìjú sì bo ojú mi.

8Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;

àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;

969.9: Jh 2.17; Ro 15.3.Nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run,

àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.

10Nígbà tí mo sọkún

tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà

èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;

11Nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà,

àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.

12Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi,

mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.

13Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni

ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa,

ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà

Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ,

dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.

14Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀,

Má ṣe jẹ́ kí n rì;

gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi,

kúrò nínú ibú omi.

15Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀

bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì

kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.

16Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ;

nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.

17Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ:

yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.

18Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là;

rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.

19Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá;

Gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.

20Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́

Mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí,

mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.

21Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi,

àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.

22Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn

ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ

fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.

23Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran,

kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.

2469.24: If 16.1.Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn;

kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.

2569.25: Ap 1.20.Kí ibùjókòó wọn di ahoro;

kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.

26Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù,

àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe

27Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn;

Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.

2869.28: If 3.5; 13.8; 17.8; 20.12,15; 21.27.Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè

kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.

29Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí,

Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.

30Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga

èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.

31Eléyìí tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ

ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.

32Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀:

Ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!

33Olúwa, gbọ́ ti aláìní,

kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.

34Kí ọ̀run àti ayé yìn ín,

Òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,

35Nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là

yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́.

Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀,

kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní.

36Àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀,

àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.