Забур 147 – CARST & YCB

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Забур 147:1-9

Песнь 147Песнь 147 В тексте оригинала песни 146 и 147 объединены в одну песнь.

1Восхваляй, Иерусалим, Вечного;

восславь, Сион, своего Бога!

2Он укрепляет затворы твоих ворот

и благословляет твоих жителей.

3Он утверждает мир в твоих пределах

и насыщает тебя отборной пшеницей.

4Он посылает Своё слово на землю;

быстро бежит Его повеление.

5Он даёт снег, как белую шерсть,

сыплет иней, как пепел,

6бросает Свой град, словно камни.

Кто может устоять перед Его морозом?

7Он посылает Своё слово, и тает всё,

подует Своим ветром, и текут воды.

8Своё слово Он возвестил потомкам Якуба,

Свои установления и законы – Исроилу.

9Для других народов Он этого не сделал;

они не знают Его законов.

Славьте Вечного!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 147:1-20

Saamu 147

1Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa,

ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!

2Olúwa kọ́ Jerusalẹmu;

Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.

3Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn

ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.

4Ó ka iye àwọn ìràwọ̀

ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ

5Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára

òye rẹ̀ kò sì ní òpin.

6Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀

bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.

7Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa

fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.

8Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀

ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé

ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè

9Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko

àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.

10Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin

bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin

11Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.

12Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu

yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.

13Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára;

Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ

14Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀

òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.

15Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé

ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.

16Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn

ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú

17Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́

ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀

18Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀

ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́

ó sì mú odò rẹ̀ sàn.

19Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu

àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli

20Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, Bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀

wọn ko mọ òfin rẹ̀.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.